Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Jèhófà Nífẹ̀ẹ́ Àwọn Èèyàn Tó Jẹ́ Mímọ́

Jèhófà Nífẹ̀ẹ́ Àwọn Èèyàn Tó Jẹ́ Mímọ́

“Lọ fọ ọwọ́ ẹ̀. Lọ fọ abọ́ tó o fi jẹun. Rí i dájú pé o gbálẹ̀. Lọ dalẹ̀ nù.” Ọ̀pọ̀ òbí máa ń kọ́ àwọn ọmọ wọn kí wọ́n lè fọwọ́ pàtàkì mú ìmọ́tótó. Àmọ́, àtọ̀dọ̀ Jèhófà Ọlọ́run mímọ́ láwọn ìlànà tó ń jẹ́ ká wà ní mímọ́ ti wá. (Ẹk 30:​18-20; Di 23:14; 2Kọ 7:⁠1) Tá a bá ń jẹ́ kí ara wa àtàwọn nǹkan ìní wa wà ní mímọ́, ṣe là ń fògo fún Jèhófà. (1Pe 1:​14-16) Ilé wa àti àyíká wa ńkọ́? Kò yẹ ká fìwà jọ àwọn èèyàn tó máa ń ju ìdọ̀tí sójú títì tàbí síbikíbi tí wọ́n bá rí. Dípò bẹ́ẹ̀, àwa Kristẹni máa ń ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe láti mú kí ilẹ̀ ayé tí Jèhófà fi jíǹkí wa wà ní mímọ́. (Sm 115:16; Ifi 11:18) Kódà nínú àwọn nǹkan kéékèèké míì irú bí ibi tá a ju ọ̀rá súìtì sí, agolo ohun mímu tàbí ṣingọ́ọ̀mù lè fi irú ọwọ́ tá a fi mú ìmọ́tótó hàn. Nínú gbogbo apá ìgbésí ayé wa ló ti yẹ ká máa “dámọ̀ràn ara wa bí òjíṣẹ́ Ọlọ́run.”​—2Kọ 6:3, 4.

WO FÍDÍÒ NÁÀ ỌLỌ́RUN NÍFẸ̀Ẹ́ ÀWỌN ÈÈYÀN TÓ JẸ́ MÍMỌ́, KÓ O SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Àwáwí wo làwọn kan máa ń ṣe tí wọn kì í fi í bójú tó àwọn nǹkan ìní wọn?

  • Báwo ni Òfin Mósè ṣe jẹ́ ká mọ ojú tí Jèhófà fi ń wo ọ̀rọ̀ ìmọ́tótó?

  • Báwo la ṣe lè fògo fún Jèhófà láìsọ ọ̀rọ̀ kan?

Báwo ni mo ṣe lè fọwọ́ pàtàkì mú ọ̀rọ̀ ìmọ́tótó bíi ti Jèhófà?