Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Ìfọkànsin Ọlọ́run Tàbí Eré Ìdárayá

Ìfọkànsin Ọlọ́run Tàbí Eré Ìdárayá

Ṣé àǹfààní wà nínú kéèyàn máa ṣeré ìdárayá? Bẹ́ẹ̀ ni, àmọ́ bíńtín ló jẹ́ tá a bá fi wéra pẹ̀lú àǹfààní tá a máa rí tá a bá ń ṣe àwọn nǹkan tó máa jẹ́ ká sún mọ́ Jèhófà. (1Ti 4:8) Torí náà, ó yẹ kí àwa Kristẹni ní èrò tó tọ́ nípa eré ìdárayá.

WO FÍDÍÒ ERÉ OJÚ PÁTÁKÓ NÁÀ OHUN TÓ YẸ KÓ O MỌ̀ NÍPA ERÉ ÌDÁRAYÁ, KÓ O SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  1. 1. Àwọn nǹkan wo la lè rí kọ́ látinú eré ìdárayá?

  2. 2. Kí ni àwọn nǹkan mẹ́ta tó máa pinnu bóyá ó máa dáa ká ṣeré ìdárayá kan tàbí ká má ṣe é?

  3. 3. Báwo ni Sáàmù 11:5 ṣe lè ràn wá lọ́wọ́ láti mọ irú eré ìdárayá tó yẹ ká ṣe?

  4. 4. Báwo la ṣe lè fi Fílípì 2:3 àti Òwe 16:18 sílò nípa ọ̀nà tá à ń gbà ṣeré ìdárayá?

  5. 5. Nígbà tá a bá ń ṣe eré ìdárayá tàbí tá à ń wò ó, báwo ni Fílípì 1:10 ṣe lè ràn wá lọ́wọ́ láti má ṣe lo àkókò tó pọ̀ jù nídìí ẹ̀?